David Ejoor

Olóṣèlú

David Akpode Ejoor RCDS, PSC, (10 January 1932 – 10 February 2019) jé̩ o̩mo̩ orílè̩-èdè Nàìjíríà,ó jẹ́ olórí Agbègbè àárín-Apá ìwọ̀-oòrùn Nàìjíríà té̩lè̩ kí ó tó di Ìpínlè̩ Bendel 1976. Ejoor tún jé̩ ọ̀gá àwọn ọmọọṣẹ́ Jagunjagun Orí-ilẹ̀ Nàìjíríà (COAS) láti ọdún 1971 di 1975.

Major General

David Akpode Ejoor
Fáìlì:Photo of David Akpode Ejoor.jpeg
Chief of Army Staff
In office
January 1971 – 29 July 1975
AsíwájúHassan Katsina
Arọ́pòTheophilus Danjuma
Commandant of the Nigerian Defence Academy
In office
January 1969 – January 1971
AsíwájúBrig M.R. Varma
Arọ́pòMaj-Gen. R.A. Adebayo
Governor of Mid-Western Region
In office
January 1966 – August 1967
AsíwájúDennis Osadebay
Arọ́pòSean Ikemefuna
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí(1932-01-10)10 Oṣù Kínní 1932.[1]
Ovu, British Nigeria
(now Delta State, Nigeria)
Aláìsí10 February 2019(2019-02-10) (ọmọ ọdún 87)
Lagos, Nigeria
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Ẹgbẹ́ olóṣèlúUnaffiliated
Military service
Allegiance Nigeria
Branch/service Nigerian Army
Rank Major general

Iṣẹ́ tó yàn láàyò

Ní ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ iṣẹ́ Ejoor, ó darí àwọn ẹ̀ṣọ́ níbi ayẹyẹ ìgbé-àsíá sóké ní òru ọjọ́ ìgbòmìnira.[2] Ejoor sọ ọ́ di mímọ̀ pé Lieutenant Colonel ìgbà náà, tí í ṣeChukwuemeka Odumegwu Ojukwu àti Ológun Yakubu Gowon wá bá òun láti sọ̀rọ̀ nípa bí wọ́n á ṣe gbìmọ̀ dìtẹ̀ lásìkò ètò ìdìbò ti ọdún 1964.[3]

[4] Ní àṣálẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní, púpọ̀ nínú àwọn òṣìṣẹ́ yìí lọ sí patí láti lọ ṣàjọyọ̀ pẹ̀lú Brigadier Zakariya Maimalari tó ń ṣe ìgbéyàwó.[5] Lẹ́yìn náà, Ejoor padà sí ilé-ìgbafẹ́ tó wà ní Ikoyi. Ó jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, pẹ̀lú òkú ẹni tí wọ́n jọ sùn sínú yàrá kan náà, ìyẹn Lieutenant-Colonel Abogo Largema, nínú ọ̀gbàrá ẹ̀jẹ̀, èyí tí Emmanuel Ifeajuna àti Godfrey Ezedigbo pa ní alẹ́ ọjọ́ náá.[6]

Ayé rẹ̀ àti ikú rẹ̀

Wọ́n bí Ejoor ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kìíní ọdún 1932 sínú ìdílé àwọn ará Urhobo ní Ovu.

Ejoor kú ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kejì ọdún 2019.[7] Ó kú nígbà tó wà ní ọmọdún mẹ́tàdínláàádọ́rùn-ún.

Àwọn Ìtọ́kasí