Atiku Abubakar

Olóṣèlú

Atiku Abubakar GCON (tí wọ́n bí ní Ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n oṣù kọkànlá ọdún 1946) jẹ́ gbajúgbajà olóṣèlú ọmọ bíbí ìpínlẹ̀ Adamawa lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Òun ni Igbákejì Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà nígbà ìṣèjọba Ààrẹ Olúṣẹ́gun Ọbásanjọ́ láti ọdun 1999 sí ọdun 2007. [1][2] Lọ́dún 2019, ó díje dupó Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà lábẹ́ àsíyá ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party tako Ààrẹ Muhammadu Buhari tí ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress, ṣùgbọ́n ìbò àti orí kò ṣe é lóore, ó fìdí remi.[3]

Atiku Abubakar
11th Vice President of Nigeria
In office
Oṣù Kàrún 29, 1999 – Oṣù Kàrún 29, 2007
ÀàrẹOlusegun Obasanjo
AsíwájúMike Akhigbe
Arọ́pòGoodluck Jonathan
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí25 Oṣù Kọkànlá 1946 (1946-11-25) (ọmọ ọdún 77)
Adamawa State, Nigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeoples Democratic Party

Ni osu kaarun odún 2022,ni won yan Atiku Abubakar gege bi oludije fun aare orílẹ̀ èdè Naijiria ti odun 2023 lábẹ́ àsíyá ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party .[4][5][6]

Láti ìgbà tí o ti wo òsèlù ní 1989, Atiku Abubakar ti díje fún ipò ààre orílè-èdè Nàìjíríà ní emarun(odun 1993, 2007, 2011, 2015 àti 2019) tí o sì fìdíremi. Ni odun 1993, o fidiremi ní idibo primari fun Moshood Abiola àti Baba Gana Kanibe.[7]

Ìdílé rẹ̀

A bí Abubakar ní 25 November 1946 sí ìlú Jẹ́daà, Ìpínlẹ̀ Adamawa.[8] Orúkọ bàbá rẹ̀ ni Garba Abubakar, ẹni tí o jẹ́ oǹtajà àti àgbẹ́ Fulani, orúkọ Ìyá Atiku sì ni Aisha Kande. A sọ Atiku Abubakar lórúkọ Bàbá-àgbà rẹ̀, ẹni tí ó ń jẹ́ Atiku Abdulqadir, o sì jẹ́ ọmọbíbí ìlú Wurno, ìpinlè Sokoto, kó tó dipé o lọ sí ìlú Jẹ́dà.

Èkó rè

Baba Atiku Abubakar lòdì sí èkó, o si gbiyanju láti mó jé kí Atiku kàwé sugbon ní ìgbà ijoba gbó nipa oro yìí, wón ti baba Atiku mon ewon fún ojo díè kí o to dipe ìyá-ìyàwó rè san owo lati gba léè. Atiku Abubakar bèrè ìwé nígbanígbà tí o jé omo odún méjo.

Abubakar lo ilé iwe Jada Primary School ni ìpínlè Adamawa. Léyìn ìgbà tí o parí èkó rè ní odún 1960, o wolé si ilé èkó Sekondiri ti Adamawa ní odun kana, pèlú omo ilé-ìwé okandinlogota(59) bi ti rè. Ni odun 1965, o keko jade ni ilé-ìwé naa, o si ni "grade three ni idanwo abajade WAEC rè.[9]Leyin ìwé sekondiri, Abubakar tèsíwájú ìwé ní Nigeria Police College ni Kaduna, sugbon o kuro léyìn ìgbà díè nitori ko fi èrí esi idanwo Mathematics rè han. Léyìn náà, o sisé agbowo ode koto dipé o wolé sí ilé-ìwé School of Hygiene ní Ìpínlè Kano ni 1966, o kó èkó jáde pèlù àmì-èye Diploma ni odun 1967.[10]Atiku tún tesiwaju ìwé léyìn èyí.

Ìdílé rè

Atiku ní ìyàwó merin àti omo mejidinlogbon.[11] Atiku so wipe: "Mo fé ní idile tí o tóbi, mo wa ni eminikan lopolopo nígbà ti mo wà lomode, mi o ní egbon tàbí àbúrò okunrin tàbí obinrin. Mi o fé kí àwon omo mi wa ní àwon nikan bi o ti jé nígbà ti mo wa lomode, óún ni mo se fé ju ìyàwó kan lo, an ìyàwó mi jé aburobinrin mi, òré mi ati olubadamoran mi, won si ún ran arawon lówó.

Ni odun 1971, Atiku fé Titilayo Albert ní ikoko, ni ìlú èkó, o fe ni ikoko nitoripe idile rè kókó tako ìfé won.[12]


Àwọn Ìtọ́kasí