Antar Laniyan
Antar Laniyan jẹ́ ògbóǹtarìgì òṣèrékúnrin, aṣàgbéjáde eré àti olùdarí eré ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1]
Antar Laniyan | |
---|---|
Ọjọ́ìbí | Osogbo, Osun, Nigeria |
Ẹ̀kọ́ | University of Ibadan, BA in theatre arts |
Iléẹ̀kọ́ gíga | University of Ibadan |
Iṣẹ́ | Film actor and producer |
Ìgbà iṣẹ́ | 1981–present |
Notable work | Sango |
Ìgbésí ayé rẹ̀
Ìlú Òṣogbo tó jẹ́ olú-ìlú Ọ̀ṣun, ní apá Ìwọ-oòrùn ilẹ̀ Nàìjíríà ni wọ́n bí Laniyan sí.[2] Ìlé-ìwé Baptist Secondary School ni ó ti gba ìwé-ẹ̀rí ( WAEC ),[3] ní Ìpínlẹ̀ Èkó kó tó di pé ó wá lọ sí Yunifásítì ìlú Ìbàdàn, láti lọ kọ́ ẹ̀kọ́ nípa iṣẹ́ tíátà.[4]
Iṣé tó yàn láàyò
Laniyan bẹ̀rẹ̀ iṣé eré-ṣíṣe ní ọdún 1981, ẹ̀dá-ìtàn àkọ́kọ́ tó sì kọ́kọ́ ṣe ni ''major general'' nínú fíìmù kan tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ Everybody wants to know lákòokòtó wà ní Kakaki Art Squad.[5][6] Ó ti kópa nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fíìmù orílẹ̀-èdè Nàìjíríà bí i Sango, èyí tó jẹ́ fíìmù tí Wale Ogunyemi ṣe, tí Obafemi Lasode sì jẹ́ olùdarí eré náà.[7][8] Òun ní olùdarí tó darí apá kìíní ti fíìmù Super Story, tí Wale Adenuga ṣàgbéjáde ní ọdún 2000, tó sì ti gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àmì-ẹ̀yẹ.[9] Òun sì ló tún darí fíìmù Oh Daughter àti This Life tí Wale Adenuga bákan náà ṣàgbéjáde.[10]
Àṣààyàn àwọn fíìmù rẹ̀
- Sango (1997)
- Super Story (episode 1)
- Kakanfo (2020)
- Lucifer (2019)