Ajàkálẹ̀-àrùn COVID-19 ní Seychelles

Ajàkálẹ̀-àrùn COVID-19 jẹ́ kíkóràn dé orílẹ̀-èdè Seychelles ní oṣù kẹ́ta ọdún 2020.[2][3] Orílẹ̀-èdè Seychelles ní àkọsílẹ̀ àwọn aláàrẹ̀ COVID-9 tí iye wọn jẹ́ mọ́kànlá ní ọgbọ̀n ọjọ́ oṣù Karùún ọdún 2020.[4]

Àrùn COVID-19 ní orílẹ̀-èdè Seychelles
ÀrùnCOVID-19
Irú kòkòrò èrànSARS-CoV-2
IbiSeychelles
Ìjásílẹ̀ àkọ́kọ́Wuhan, China
Index casePerseverance Island
Arrival date11 March 2020
(4 years and 3 months)
Gbogbo iye àwọn ẹ̀sùn114[1]
Iye àwọn tí ara wọn ti yá69 (As of 25 July 2020)
Iye àwọn aláìsí
0 (As of 30 May 2020)

Àwọn àsìkò tí ó ń ṣẹlẹ̀

Àdàkọ:COVID-19 pandemic data/Seychelles medical cases chart

Oṣù kẹ́ta ọdún 2020

Orílẹ̀-èdè Seychelles kéde akọsílẹ̀ ajàkálẹ̀ àrùn COVID-9 rẹ̀ ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹta lára àwọn ènìyàn méjì tí wọ́n fara kó àrùn yí lára ẹ́nìkan tí ó ti ní àrùn yí tẹ́lẹ̀ ní Orílẹ̀-èdè Italy[5]Ní ọjọ́ kẹéẹ́dógún oṣù kẹta, wọ́n ní akọsílẹ̀ ẹnìkẹta tí tí ó kó àrùn náà nígbà tí ó ń bọ̀ láti orílẹ̀-èdè Netherlands.[6]Àwọn ẹlòmíràn náà tún ní àrùn yí nígbà tí àwọn náà ń darí bọ̀ láti orílẹ̀-èdè Netherlands yí kan náà.[7]

Nígbà tí oṣù náà yóò fi parí, àwọn mẹ́wàá ni ayéwò rẹ̀ ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ wípé wọ́n ti ní àrùn Kòrónà ní orílẹ̀-èdè Seychelles tí ẹnikẹ́ni kò sì kú.[8]

Oṣù kẹrin ọdún 2020

Ní ọjọ́ kẹfà oṣù kẹrin ọdún 2020, wọ́n ṣe ìtọ́jú àwọn ènìyàn méjì nínú àwọn aláàrẹ̀ COVID-9, tí wọ́n sì padà sí ilé wọn láyọ̀.[9]

Níparí oṣù kẹrin, àwọn ènìyàn mẹ́rin ninú àwọn aláàrẹ̀ COVID-9, ni wọ́n rí ìtọ́jú gbà tí wọ́n sì padà sí ilé wọn láyọ̀. Ò sì ku àwọn márùún gedengbe tí wọ́n kù tí wọn sì wà lórí àárẹ̀ náà.[10]

Oṣù Karùún ọdún 2020

Ní oṣù Karùún, ìjọba orílẹ̀-èdè Seychelles kéde wípé kò sí ajàkálẹ̀ àrùn COVID-9 ní orílẹ̀-èdè náà mọ́ bí ó ti wulẹ̀ kí ó kéré mọ. Nígbà tí yóò fi di ọjọ́ kejìdínlógún oṣù Karùún, gbogbo àwọn aláàrẹ̀ náà ti gbádùn tán pátá pátá. [11]

Oṣù Kẹfà ọdún 2020

Ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹfà, wọ́n tún rí akọsílẹ̀ àwọn ènìyàn míràn tí wọ́n jẹ́ aláàrẹ̀ COVID-9 tí iye wọn tó mọ́kàndínlọ́gọ́ta, méje míràn ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n ati mẹ́rin míràn ní ọgbọ̀njọ́ oṣù Kẹfà tí ó mú kí iye gbogbo wọn jẹ́ ogójì lápapọ̀ nínú oṣù Kẹfà nìkan. [12] Iye àwọn ènìyàn tí wọ́n ti ní àrùn COVID-9 láti ìbẹ̀rẹ̀ jẹ́ mọ́kànléláàdọ́rin lápapọ̀, tí àwọn mọ́kanlá ti gba ìtọ́jú tí wọ́n sì padà sí ilé wọn láyọ̀. Ó ku àwọn àádóje ènìyàn tí wọn ṣì ń bá àárẹ̀ náà jà., níparí oṣù kẹfà. [13] All 70 had previously tested negative in Abidjan or Dakar but positive on arrival in Seychelles.[14]

Oṣù keje ọdún 2020

Wón tún ní akọsílẹ̀ mélòó kan tí wọ́n tí ó tó mẹ́talá tí ó mú kí gbogbo iye àwọn tí ó ní àrùn yí gùnkè sí mẹ́rìnlélàádósán, tí àwọn mẹ́talá sì jẹ́ ará ilẹ̀ òkèrè.[15]Wọ́n tún rí àìsan yí lára àwọn ènìyàn mẹ́fà míran tí wọ́n jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Seychelles, tí ó mú iye àwọn aláàrẹ̀ náà lápapọ̀ ó jẹ́ ọgọ́rùún.[16] By 22 July all six local patients had recovered.[17] Iye àwọn aláàrẹ̀ náà ti di mẹ́rìnlélọ́gọ́rùún nígbà tí àwọn mọ́kandínlógójì ènìyàn sì rí ìwòsàn gbà níparí oṣù kẹfà.[18]

Ìgbésẹ̀ ìjọba

Ìfagilé lílọ-bíbọ̀

Ní ọjọ́ kẹsàán oṣù kẹta ọdún 2020, ìjọba ilẹ̀ Seychelles ti ẹnu ibodè wọn ní orí omi àti cruise ships.[19] Ní ọjọ́ kẹsàán oṣù kẹta ọdún 2020, orílẹ̀-èdè Seychelles fagilé ìrìn-àjò àwọn ènìyàn láti lọ sí orílẹ̀-èdè China, South Korea, Italy ati Iran àmọ́ wọ́n fi ayè gba àwọn tí wọ́n bá fẹ́ padà wá sílé.[19]

Ọkùnrin ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún tí ó jẹ́ òṣìṣẹ́ ilé-iṣẹ́ pápákọ̀ òfurufú kan náà ní àrùn yí tí ó mú kí iye àwọn aláàrẹ̀ arùn Kòrónà ó di mọ́kànlá ní inú oṣù kẹ́rin. Lẹ́yìn tí wọ́n ṣàkíyèsí èyí ni wọ́n ṣe òfin kónílé-ó-gbélé fún gbogbo ènìyàn ayàfi àwọn òṣìṣẹ́ tí iṣè wọn ṣe kókó jùlọ. Òfin yí yóò bẹ́rẹ́ iṣẹ́ ní alẹ́ ọjọ́rú ọjọ́ kẹjọ oṣù kẹ́rin ọdún 2020, yoo sì wà ní lílò títí di ọjọ́ mọ́kànlélógún gbáko. [20] It opened again to scheduled traffic on 1 August.[21]

Ilé Ìṣẹ̀mbáyé

Lẹ́yìn tí wọ́n sòfin kónílé-ó-gbélé ní ọjọ́ kẹsàán oṣù kẹ́rin ọdún 2020, ilé-iṣẹ́ tí ó ń mójú tó ilé ìṣẹ̀mbáyé ń múra láti ṣí ilé ọ̀hún padà fún àwọn ènìyàn ní ọjọ́ Kíní oṣù Kẹfà ọdún 2020, fúndí èyí orílẹ̀-èdè Seychelles ni yóò jẹ́ orílẹ̀-èdè akọ́kọ́ tí yóò ṣí ilé ìṣẹ̀mbáyé fún àwọn ènìyàn lásìkò ìtànkálẹ̀ ajàkálẹ̀ àrùn COVID-9 ní apá àríwá ilẹ̀ Afirikà. [22]

Kí gbogbo ilé-iṣẹ́ ati okòwò ó tó lè bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ òòjọ́ padà, ilé-iṣẹ́ ìjọba tí ó ń rí sí ètò ìlera wọ́n ní láti ṣe àgbékalẹ̀ àwọn ìlàna àti ààtò kọ̀ọ̀kan kalẹ̀ láti lè dá ààbò bo àwọn òṣìṣẹ́ ilé ìṣẹ̀mbáyé náà àti àwọn olùbẹ̀wò ibẹ̀ gbogbo kí wọ́n má ba ma pín àrùn fúnra wọn.[22] Lára awọn ìlànà àti ààtò náà ni wípé : mímójú tó iye ènìyàn tí yóò ma wọ ilé ìṣẹ̀mbáyé lásìkò kan náà. Fagilé ìgbẹ̀wò míràn bí ó bá ṣe é ṣe. Ṣíṣe ìmọ́tótó àyíkà gbogbo, àti ìtọ́jú òun ìrànwọ́ fún àwọn òṣìṣẹ́ náà. [22]

Mímú ìdẹ̀rùn bá àwọn òfin

Ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹ́rin, Ààrẹ ilẹ̀ orílẹ̀-èdè Seychelles ọ̀gbẹ́ni Danny Faure kéde wípé ìjọba ti ṣetán láti mú ìdẹ́rùn bá àwọn ará Ìlú lórí àwọn òfin tí wọ́n ti ṣe láti lè dẹ́kun ìtànkálẹ̀ ajàkálẹ̀ arùn COVID-9 ní orílẹ̀-èdè náà. Wọ́n gbójú kúrò luru òfin ìrìnà ní ọjọ́ kẹrin oṣù Karùún ọdún 2020, nígbà tí wọ́n tún fàyè gba àwọn ilé-ìtajà gbogbo láti ma bá iṣẹ́ okòwò wọn lọ ní ọjọ́ yí kan náà láti àárọ̀ títí di agogo mẹ́jọ alẹ́. Wọ́n ṣí àwọn ilé-ẹ̀kọ́ gbogbo padà ní ọjọ́ kọkànlá àti ọjọ́ kejìdínlógún oṣù Karùún. Wọ́n sì fòpin sí gbogbo àwọn òfin náà ní ọjọ́ Kíní oṣù kẹfà ọdún 2020[23]

Air Seychelles resumed domestic flights on May 4, and SEI reopened to international traffic on June 1.[24]

Gbèdéke lórí ìrìn-àjò lọ sókè òkun

Ní ọjọ́ kẹsàán oṣù Karùún, ìjọba orílẹ̀-èdè Seychelles fagilé ìwọlé sí orílẹ̀-èdè wọn láti ẹnu ibodè Victoria títí di ìparí ọdún 2021. [25] Àwọn ènìyàn tí wọ́n bá darí sí orílẹ̀-èdè Seychelles láti orí ọkọ̀ ojú-omi, wọ́n ní láti wà ní iyàrá àdágbé fún ọjọ́ fún ọjọ́ mẹ́rìnlá gbáko. Nígbà tí àwọn àwọn tí wọ́n bá darí láti orí ọkọ̀ òfurufú, wọ́n ní láti ṣe ayéwò láàrín ọjọ́ méjì kí wọ́n tó dá wọn sílẹ̀.[11]

Ẹ tún lè wo

Àwọn Ìtọ́kasí

Àdàkọ:COVID-19 pandemic