Àjàkálẹ̀-àrùn COVID-9 ní Kamẹrúùnù

Àjàkálẹ̀ Àrùn COVID-9 dé orílẹ̀-èdè Kamẹrúùnù ní inú oṣù Kẹ́ta ọdún 2020.

Àjàkálẹ̀ Àrùn COVID-9 ní orílẹ̀-èdè Cameroon
Confirmed cases by region títí di 2 Oṣù Kẹfà 2020 (2020 -06-02).
ÀrùnCOVID-19
Irú kòkòrò èrànSARS-CoV-2
IbiKamẹrúùnù
Ìjásílẹ̀ àkọ́kọ́Wuhan, China
Index caseYaoundé
Arrival date6 March 2020
(4 years, 3 months and 6 days)
Gbogbo iye àwọn ẹ̀sùn16,522 (as of 23 July)[1]
Active cases2,412 (as of 23 July)
Iye àwọn tí ara wọn ti yá13,728 (as of 23 July)
Iye àwọn aláìsí
382 (as of 23 July)
Territories
Bafoussam, Douala & Yaounde
Official website
covid19.minsante.cm

Bí ó ṣe bẹ̀rẹ̀

Ní ọjọ́ Kejìlá oṣù Kíní ọdún 2020, Àjọ ìṣọ̀kan tí ó ń rí sí ìlera ní àgbáyé fìdí àrùn Kòrónà tí a tún ń pè ní Kofid-19 ní orílẹ̀-m àgbáyé ní ọjọ́ Kejìlá oṣù Kínní ní ọdún 2020. Tí wọ́n sì fìdí rẹ̀ múlẹ̀ wípé àrùn yí bẹ̀rẹ̀ ní ìlú kan tí wọ́n ń pè ní Wuhan, ní ẹkùn Hubei ní orílẹ̀-èdè China. Àmọ́ ó tó ọjọ́ Kẹtalélọ́gbọ̀n oṣù Kejìlá ọdún 2019 kí wọ́n tó fi tó àjọ ìṣòkan àgbáyé létí.[2][3]

Wọ́n tún fìdí rẹ̀ múlẹ̀ siwájú si wípé bí àrùn yí bá ti mú ènìyàn, oun ni ó ń fa ìfúnpinpin ní ní inú káà ọ̀fun ati àyà, tí ó sì ma ń fa kàtá tàbí kí ènìyàn ó ma wú ikọ́ tàbí sín léra léra. Iye ìjàmbá tí àrùn Kòrónà ti fà lágbáyé kéré sí iye ìjàmbá tí àìsàn àrùn ọ̀fun SARS ti fà láti ọdún 2003. Àmọ́ iye àwọn ènìyàn tí wọ́n tó àrùn Kòrónà látàrí ríràn tí ó ń ràn kálẹ̀ ti.pọ̀ ju ti SARS lọ, bí ó ti lẹ̀ jẹ́ wípé ìtànkálé àrùn COVID-19 ń gbópọn si lójojúmọ́ tí ó sì ti ṣekú pa ọ̀pọ̀lọpò ènìyàn lágbáyé,[4][5][6][4]

Àwọn àsìkò kọ̀ọ̀kan tí ò ṣẹlẹ̀

Oṣù Kẹ́ta ọdún 2020

Àjàkálẹ̀ àrùn COVID-9 wọ orílẹ̀-èdè Cameroon ní ọjọ́ Kẹfà oṣù kẹ́ta ọdún 2020 nígbà tí wọ́n ní akọsílẹ̀ akọ́kọ́ láti ara ẹnìkan tí ó ti ní àrùn yí tí ó jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Faranse tí ó wọ ìlú Yaounde ní orílẹ̀-èdè Cameroon ní ọjọ́ Kẹrìnlélógún oṣù kejì. [7][8][9][10]

Akọsílẹ̀ kejì ni wọ́n kéde rẹ̀ ní ọjọ́ Kẹfà oṣù kẹ́ta lára ẹnikan tí ó jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Cameroon tí ó ti ní ìfara-kínra pẹ̀lú ẹni akọ́kọ́ tí kọ́kọ́ kó arùn náà wọ Cameroon tẹ́lẹ̀.[11]Wọ́n tún ní àkọsílẹ̀ márùún míràn ní ọjọ́ kejìdínlógún oṣù kẹta, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wípé wọn kò fi ìtọ́ka kankan léde nípa àwọn ènìyàn náà.[12]Mínísítà fún ètò ìlera ní orílẹ̀-èdè Cameroon ìyẹn Dókítà Malachie Manaouda, sọ wípé àrùn náà ń gbilẹ̀ si lójoojúmọ́ ni pẹ̀lú bí wọ́n tún ṣe rí akọsílẹ̀ mẹ́rìdínlógún mìíràn tí mẹ́fà wá.láti Yaounde, mẹ́sàán láti Ìlú Douala, tí ẹyọ̀kan sì wá láti Bafoussam.[13]

Ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹta, wọn ti ní akọsílẹ̀ tí ó tó mọ́kàndílọ́gọ́rùún. Mẹ́tàlélọ́gọ́ta láti Yaounde, márùndínlọ́gbòn ní Douala, tí mẹ́ta sì wá láti Bafoussam.[14][15][16][17]

Gbogbo iye àwọn aláìsàn COVID-9 lápapọ̀ nínú oṣù kẹta jẹ́ ọgọ́rùún kan ó lé mẹ́jìlélógójì ní ìparí oṣù kẹta, nígbà tí iye àwọn ènìyàn mẹ́fà papò dà.[18]

Oṣù Kẹrin ọdún 2020

Nígbà tí yóò fi di ọjọ́ kẹfa oṣù kẹrin, iye àwọn ènìyàn tí wọ́n ti kó àrùn COVID-9 jẹ́ ọgọ́rùún méjì àti mẹ́fàlélọ́gọ́jọ.[19]Àrùn naa sì tún mú iye ènìyàn tí ó ọgọ́rùún mẹ́fà àti méjìdínlọ́gọ́ta ní ọjọ́ kẹfa oṣù kẹrin.[20]Ó tún gòkè si ní ọjọ́ keje oṣù yí kan nàá oẹ́lú iye tí ó tó ọgọ́rùún mẹ́fà àti márùndínlọ́sàán.[21]Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹrin, ó tún gòkè si pẹ́lú iye tí ó tó ọgọ́rùún méje àti ọgbọ̀n.[22]Ní ọjọ́ karùlélógún oṣù kẹrin, wọ́n ti ní akọsílẹ̀ tí ti tó ẹgbẹ̀rún kan ólé ọgọ́rùún márùún àti mẹ́tàlá ènìyàn tí wọ́n ti lu gúdẹ àrùn náà ní orílẹ̀-èdè Cameroon. [23]Iye àwọn tí wọ́n kó àrùn náà ní ú oṣù kẹrin lápapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé ọgọ́jọ àti méjìlélọ́gbọ̀n. Iye àwọn ènìyàn tí wọ́n gba ìwòsàn lápapọ̀ jẹ́ ọgọ́rùún mèsàán ó lé mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, nígbà tí iye ènìyàn tó kù tí kò tí rí ìwòsàn gba tí wọn kò sì papò dà jẹ́ ọgọ́rùún mẹ́jọ ó lé mẹ́tàdínlógójì. [24]

Oṣù Karùún ọdún 2020

Wọ́n ní akọsílẹ̀ tí tó ẹgbẹ̀rún méjì ati mẹ́rìnlélọ́gọ́rùún, tí ènìyàn mẹ́rìnlélọ́gọ́ta sì gbẹ́mí mì. [25]Iye akọsílẹ̀ tí wọ́n ní nínú oṣù kẹrin jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́rin méjìlélọ́gọ́rin tí ó sì mú kí akọsílẹ̀ náà tó ẹgbẹ̀rún márùún ati mẹ́rìnlélọ́gọ́sàán. Iye àwọn ènìyàn tí wọ́n gba ìmúlára dá lápapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ati ọgọ́rùn márùún ó lé méjìdínlógóje. [26]

Oṣù Karùún ọdún 2020

Wọ́n rí akọsílẹ̀ tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ó lé méjìdínlógóje, nígbà tí iye àwọn ènìyàn tí rí ìwòsàn gba jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lápapọ̀. Iye àwọn ènìyàn tí kò kú tí kò sì gbádùn jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ọgọ́rùún kan ó lé mọ́kàndínlọ́gọ́jọ.[27]

Akọsílẹ̀ iye ènìyàn tó ti papò dà

Oṣù Kẹ́ta ọdún 2020

Ẹni akọ́kọ́ tí kọ́kọ́ gbẹ́mìí mì kú ní ọjọ́ Kẹrìnlélógún oṣù kẹta. [28] the deceased was the famous saxophonist Manu Dibango.[29] By the end of March six persons had died from COVID-19.[30]

Oṣù Kẹrin ọdún 2020

Ènìyàn mẹ́rìndínláàdọ́rin ni ó papò dà nínú oṣù kẹrin.tí ó sì jẹ́ kí gbogbo rẹ̀ ó bọ́ sí mọ́kanlélọ́gọ́ta.[24]

Oṣù Karùún ọdún 2020

Iye ènìyàn tí ó kú nínu oṣù Karùún jẹ́ ọgọ́rùún kan àti ọgbọ̀n tí ó mú kí gbogbo iye ènìyàn tí papò dà ó jẹ́ 191.[26]

Oṣù Kẹfà ọdún 2020

Àwọn ọgọ́rùún kan ólé mẹ́jìlélógún ènìyàn ló kú tí ó mú kí gbogbo iye ènìyàn tí papò dà ó jẹ́ ọgọ́rùún kan ó lé mẹ́tàlélọ́gọ́ta lápapọ̀. [27]

Ìrànwọ́ Oògùn ati irinṣẹ́ ìlera

Ọ̀gbẹ́ni Jack Ma ṣe ìrànwọ́ nípa fífi àwọn nkan irinṣẹ́ ìlera ìgbalódé bí irinṣẹ́ ayẹ̀wò tí ó tó 9gọ́rùún lọ́nà ogún, ìbòjú tí ó tó ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rùún àti àwọn irinṣẹ́ ìdáàbò bò àwọn òsìṣẹ́ ìlera míràn tí ó tó ẹgbẹ̀rún kan láti gbógun ti àjakálẹ̀ àrùn Kòrónà ní ilẹ̀ Áfíríkà[31] The supplies arrived to Cameroon's Yaounde Nsimalen Airport on 27 March.[32]

Gbajú-gbajà agbá bọ́ọ̀lù aláfẹsẹ̀ gbá ìyẹn Samuel Eto'o ṣe ìrànwọ́ ìbòjú tí ó tó ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta fún àwọn ọlọ́kọ̀ èrò ní ìlú rẹ̀.[33]

Ìgbésẹ̀ àwọn Ìjọba

Ní ọjọ́ kejìdínlógún oṣù kẹta ọ̀gbẹ́ni Joseph Dion Ngute tí ó jẹ́ olórí àwọn mínísítà fún orílẹ̀-èdè Cameroon pàṣẹ pé kí wọ́n ti gbogbo ẹnu ibodè tí ó wọ Ìlú wọn pátá.[34]Mínísítà fún ètò ìlera kéde rẹ̀ ní ọgnọ̀njọ́ oṣù kẹrin wípé àwọn òṣìṣẹ́ ìlera yóò ma lọ láti ojúlé sí ojúlé láti ṣàyẹ̀wò àrùn COVID-9 fún àwọn ènìyàn, èyí ni láti tètè dẹ́kun ìtànkálẹ̀ àrùn náà ní ìlú Douala láti ọjọ́ kejì sí ọjọ́ kẹfà oṣù kẹ́rin. [35]Ní ọjọ́ keje oṣù kẹ́rin, ìjọba orílẹ̀-èdè Cameroon kóra-ró lórí ìtọrọ ìrànwọ́ lọ́wọ́ àwọn lààmì-laaka lágbàáyé àti àwọn ọ̀tọ̀kùlú-ìlú láti gbógun ti àjakálẹ̀ àrùn COVID-9. Ìgbésẹ̀ yí mú ìkùnsínú wá láti ọ̀dọ̀ àwọn ará ìlú lọ́pọ̀lọpọ̀ ònà, tí wọ́n sì lí ìgbésẹ̀ náà mọ́ ẹbọ òṣèlú.[36]Ọjọ́ Kẹwàá oṣù kẹrin yí kan náà ni ìjọba orílẹ̀-èdè Cameroon gbé ìgbésẹ̀ onípele méje kan láti dẹ́kun ìtànkàlẹ̀ àrùn Kòrónà ní orílẹ̀-èdè wọn. Ìgbésẹ̀ yí bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ Ajé sí ọjọ́ kẹtalá oṣù kẹ́rin ọdún 2020.[37]

  • Ìgbésẹ̀ Kíní: Ìpọn dandan láti wọ ìbòjú ní àwùjọ gbogbo;
  • Ìgbésẹ̀ Kejì: Pípèsè oògùn lábẹ́lé, ṣíṣe àyẹ̀wò , ṣíṣe ìbòjú àti ọṣẹ ìfọwọ́ olómi;
  • Ìgbésẹ̀ Kẹta: Dídá ilé-ìwòsàn tí wọn yóò ti ma ṣe àyẹ̀wò arùn COVID-9 ní gbogbo olú ìlú àti ìgbèríko wọn;
  • Ìgbésẹ̀ Kẹrin: Títẹpẹlẹ mọ́ ìpolongo nípa àrùn náà fún àwọn ará ìlú kí wọ́n lè mọ ohun tí ó ṣe pàtàkì nípa arùn náà;
  • Ìgbésẹ̀ Karùún: Títẹpẹlẹ mọ́ ìpolongo nípa àrùn náà fún àwọn ará ìlú ní àwọn ìgbèríko àti àrọko, ní oríṣiríṣi èdè tí wọ́n gbọ́ kí wọ́n lè mọ ohun tí ó ṣe pàtàkì nípa arùn náà;
  • Ìgbésẹ̀ Kẹfà: Mímú ìtẹ̀síwájú tó nípọn bá àwọn àwọn okòwò láti ri wípé wọ́n tẹ̀lér àwọn àlakalẹ̀ ìjọba láti ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kẹta ọdún 2020.
  • Ìgbésẹ̀ Keje: Ìbàwí tó gbópọn fún.ẹnikẹ́ni tó bá tàpá sófin.

Ní ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù kẹta, Ààrẹ ẹgbẹ́ àwọn adájọ́ Paul Biya kéde ré wípé ilé-ẹjọ́ gbé ìgbésẹ̀ bíbojú àánú wo àwọn ẹlẹ́wọ̀n nípa títú wọn sílẹ̀ kí ọgba ẹ̀wọ̀n lè fúyẹ́ kí àjakálẹ̀ arùn Kòrónà má ba fibẹ̀ ṣe ibùgbé ayérayé.[38]

On Tuesday May 5, the Minister of Health announced the provision to healthcare personnel of 50,000 coveralls, 320,000 surgical masks, 220 backpack sprayers, 10,000 pairs of overshoes.[39]Nígbà tí oṣù Kẹfà ń parí lọ, ìjọba orílẹ̀-èdè Cameroon kéde wípé ìdíje bọ́ọ̀lù apapọ̀ ilẹ̀ Adúláwọ̀ ti 2021 kò ní lè wáyé mọ́ títí di ọdún 2022, látàrí àjakálẹ̀ arùn COVID-9.[40]

Ẹ tún lè wo

Àdàkọ:Portal bar

Àwọn Ìtọ́kasí

Àwọn Ìtàkùn ìjásòde

Àdàkọ:COVID-19 pandemic